Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 1:22-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

22. Sílífà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́,ààyò wáìnì rẹ la ti bomi là.

23. Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín,akẹgbẹ́ àwọn olè,gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri.Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba,ẹjọ́ opó kì í sìí dé iwájú wọn.

24. Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogunAlágbára kanṣoṣo tí Ísírẹ́lì sọ wí pé:“Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá min ó sì gbẹ̀ṣan lára àwọn ọ̀tá mi.

25. Èmi yóò pa ọwọ́ mi dà sí ọ,èmi ó sì ku ìpẹ́pẹ́ rẹ dànù,n ó sì mú gbogbo ìdọ̀tí rẹ kúrò.

26. Èmi yóò mú àwọn adájọ́ rẹ bọ̀sípò gẹ́gẹ́ bí i ti àtijọ́,àti àwọn olùdámọ̀ràn rẹ̀ bí i ti ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀.Lẹ́yìn náà ni a ó pè ọ ní ìlú òdodo, ìlú òtítọ́.”

27. A ó fi ìdájọ́ òtítọ́ ra Ṣíhónì padà,àti àwọn tí ó ronú pìwàdà pẹ̀lú òdodo.

28. Ṣùgbọn àwọn ọlọ̀tẹ̀ àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó pa runÀwọn tí ó bá sì kọ Olúwa sílẹ̀ ni yóò ṣègbé.

29. “Ojú yóò tì yín nítorí igi óákù mímọ́èyí tí ẹ ní inú dídùn sía ó kàn yín lábùkù nítorí àwọn ọgbà yìítí ẹ ti yàn fúnra yín.

30. Ẹ ó sì dàbí igi óákù tí ewé rẹ̀ tí,tàbí bí ọgbà tí kò ní omi.

31. Alágbára ọkùnrin náà yóò sì dàbí lẹ́ùiṣẹ́ rẹ̀ bí ẹ̀ṣẹ́-iná,àwọn méjèèjì ni yóò jóná papọ̀,láì sí ẹni tí yóò lè pa iná yìí.”

Ka pipe ipin Àìsáyà 1