Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 8:5-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Nígbà tí àwọn ará Síríà ti Dámásíkù sì wá láti ran Hadadésérì ọba Sóbà lọ́wọ́, Dáfídì sì pa ẹgbàámọ́kànlá ènìyàn nínú àwọn ará Síríà.

6. Dáfídì sì fi àwọn ológún sí Síríà ti Dámásíkù: àwọn ará Síríà sì wá sin Dáfídì, wọn a sì máa mú ẹ̀bùn wá, Olúwa sì pa Dáfídì mọ́ níbikíbi tí o ń lọ.

7. Dáfídì sì gba àṣà wúrà tí ó wà lára àwọn ìránṣẹ Hadadésérì, ó sì kó wọn wá sí Jérúsálẹ́mù.

8. Láti Bétà, àti láti Bérótáì, àwọn ìlú Hadadésérì, ni Dáfídì ọba sì kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ baba wá.

9. Nígbà tí Tóù ọba Hámátì sì gbọ́ pé Dáfídì ti pa gbogbo ogun Hadadésérì.

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 8