Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 8:13-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Dáfídì sì ní òkìkí gidigidi nígbà tí ó padà wá ilé láti ibi pípa àwọn ará Síríà ní àfonífojì iyọ̀, àwọn tí o pa jẹ́ ẹgbaàsán ènìyàn.

14. Ó sì fi àwọn ológun sí Édómù; àti ní gbogbo Édómù yíká ni òun sì fi ológun sí, gbogbo àwọn tí ó wà ní Édómù sì wá sin Dáfídì, Olúwa sì fún Dáfídì ní ìṣẹgún níbikíbi tí ó ń lọ.

15. Dáfídì sì jọba lórí gbogbo Ísírẹ́lì; Dáfídì sì ṣe ìdájọ́ àti òtítọ́ fún àwọn ènìyàn rẹ̀.

16. Jóábù ọmọ Sérúyà ni ó sì ń ṣe olórí ogun; Jéhóṣáfátì ọmọ Áhílúdì sì ń ṣe akọ̀wé.

17. Sádókù ọmọ Áhítúbì, àti Áhímélékì ọmọ Ábíátarì, ni àwọn àlùfáà; Sérúyà a sì máa ṣe akọ̀wé.

18. Bénáyà ọmọ Jéhóíádà ni ó sì ń ṣe olórí àwọn Kérétì, àti àwọn Pélétì; àwọn ọmọ Dáfídì sì jẹ́ aláṣẹ.

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 8