Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 8:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ó sì ṣe, lẹ́yìn èyí, Dáfídì sì kọlu àwọn Fílístínì, ó sì tẹrí wọn ba: Dáfídì sì gba Metegamímà lọ́wọ́ àwọn Fílístínì.

2. Ó sì kọlu Móábù, ó sì fi okùn títa kan dìwọ́n, ó sì dá wọn dùbúlẹ̀; ó sì ṣe òṣùwọ̀n okùn méjì ni iye àwọn tí yóò dá sí. Àwọn ará Móábù sì ń sin Dáfídì, wọn a sì máa mú ẹ̀bùn wá.

3. Dáfídì sì kọlu Hadadésérì ọmọ Rehóbù, ọba Sóbà, bí òun sì ti ń lọ láti mú agbára rẹ̀ bọ̀ sípò ni odò Éfúrétì.

4. Dáfídì sì gba ẹgbẹ̀rún kẹ̀kẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀, àti ẹ̀ẹ́dẹ̀gbẹ̀rin ẹlẹ́ṣin, àti ẹgbàawá àwọn ẹlẹ́sẹ̀: Dáfídì sì já gbogbo àwọn ẹṣin kẹ̀kẹ́ wọn ní pátì, ṣùgbọ́n ó dá ọgọ́rún kẹ̀kẹ́ sí nínú wọn.

5. Nígbà tí àwọn ará Síríà ti Dámásíkù sì wá láti ran Hadadésérì ọba Sóbà lọ́wọ́, Dáfídì sì pa ẹgbàámọ́kànlá ènìyàn nínú àwọn ará Síríà.

6. Dáfídì sì fi àwọn ológún sí Síríà ti Dámásíkù: àwọn ará Síríà sì wá sin Dáfídì, wọn a sì máa mú ẹ̀bùn wá, Olúwa sì pa Dáfídì mọ́ níbikíbi tí o ń lọ.

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 8