6. Wọ́n sì wá sí Gílíádì, àti sí ilé Tátímhódíṣì; wọ́n sì wá sí Dan-Jaanì àti yíkákiri sí Sídónì,
7. Wọ́n sì wá sí ìlú olodi Tírè, àti sí gbogbo ìlú àwọn Hífì, àti ti àwọn ará Kénánì: wọ́n sì jáde lọ síhà gúsù ti Júdà, àní sí Bééríṣébà.
8. Wọ́n sì la gbogbo ilẹ̀ náà já, wọ́n sì wá sí Jérúsálẹ́mù ní òpin oṣù kẹsàn-án àti ogúnjọ́.
9. Jóábù sì fi iye tí àwọn ènìyàn náà jásí lé ọba lọ́wọ́: ó sì jẹ́ òjì ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára ní Ísírẹ́lì, àwọn onídà: àwọn ọkùnrin Júdà sì jẹ́ ọkẹ mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n ènìyàn.