Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 20:22-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

22. Obìnrin náà sì mú ìmọ́ran rẹ̀ tọ gbogbo àwọn ènìyàn náà, wọ́n sì bẹ Ṣébà ọmọ Bíkírì lórí, wọ́n sì sọ ọ́ sí Jóábù. Òun sì fún ìpè, wọ́n sì túká sọ́dọ̀ ọba.

23. Jóábù sì ni olórí gbogbo ogun Ísírẹ́lì: Bénáyà ọmọ Jéhóiádà sì jẹ́ olórí àwọn Kérétì, àti ti àwọn Pélétì.

24. Ádórámù sì jẹ́ olórí àwọn agbowó òde: Jéhóṣáfátì ọmọ Áhílúdì sì jẹ́ olùkọsílẹ̀ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ ní ìlú.

25. Ṣéfà sì jẹ́ akọ̀wé: Sádókù àti Ábíátarì sì ni àwọn àlùfáà.

26. Írà pẹ̀lú, ará Jáírì ni ń ṣe àlùfáà lọ́dọ̀ Dáfídì.

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 20