Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 20:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọkùnrin Bélíálì kan sì ń bẹ níbẹ̀ orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣébà ọmọ Bíkírì ará Bẹ́ńjámínì; ó sì fún ìpè ó sì wí pé,“Àwa kò ní ipa nínú Dáfídì,bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ni ìní nínú ọmọ Jésè!Kí olúkúlùkù ọkùnrin lọ sí àgọ́ rẹ̀, ẹ̀yin Ísírẹ́lì!”

2. Gbogbo àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì sì lọ kúrò lẹ́yìn Dáfídì, wọ́n sì ń tọ́ Ṣébà ọmọ Bíkírì lẹ́yìn: ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Júdà sì fi ara mọ́ ọba wọn láti odò Jódánì wá títí ó fi dé Jérúsálẹ́mù.

3. Dáfídì sì wà ní ilé rẹ̀ ní Jérúsálẹ́mù; ọba sì mú àwọn obìnrin mẹ́wàá tí í ṣe àlè rẹ̀, àwọn tí ó ti fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ile, Ó sì há wọn mọ́ ilé, ó sì ń bọ́ wọn, ṣùgbọ́n kò sì tún wọlé tọ̀ wọ́n mọ́. A sì ṣé wọn mọ́ títí di ọjọ́ ikú wọn, wọ́n sì wà bí opó.

4. Ọba sì wí fún Ámásà pé, “Pè àwọn ọkùnrin Júdà fún mi níwọn ijọ́ mẹ́ta òní, kí ìwọ náà kí o sì wà níhìnyìí.”

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 20