Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 18:4-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ọba sì wí fún wọn pé, “Èyí tí ó bá tọ́ lójú yin ni èmi ó ṣe.”Ọba sì dúró ní apákan ẹnu odi, gbogbo àwọn ènìyàn náà sì jáde ní ọrọrún àti ní ẹgbẹẹgbẹ̀rún.

5. Ọba sì pàṣẹ fún Jóábù àti Ábíṣáì àti Ítaì pé, “Ẹ tọ́jú ọ̀dọ́mọkùnrin náà Ábúsálómù fún mi.” Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì gbọ́ nígbà tí ọba pàṣẹ fún gbogbo àwọn balógun nítorí Ábúsálómù.

6. Àwọn ènìyàn náà sì jáde láti pàdé Ísírẹ́lì ní pápá; ní igbó Éfúráímù ni wọ́n gbé pàdé ijà náà.

7. Níbẹ̀ ni a gbé pa àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì níwájú àwọn ìránṣẹ́ Dáfídì, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni ó ṣubú lọ́jọ́ náà, àní ẹgbàáwá ènìyàn.

8. Ogun náà sì fọ́n káàkiri lórí gbogbo ilẹ̀ náà: igbó náà sì pa ọ̀pọ̀ ènìyàn ju èyí tí idà pa lọ lọ́jọ́ náà.

9. Ábúsálómù sì pàdé àwọn ìránṣẹ́ Dáfídì. Ábúsálómù sì gun orí ìbaka kan, ìbaka náà sì gba abẹ́ ẹ̀ka ńlá igi óákù kan tí ó tóbi lọ, orí rẹ̀ sì kọ́ igi óákù náà òun sì rọ̀ sókè ní agbede-méjì ọ̀run àti ilẹ̀; ìbaka náà tí ó wà lábẹ́ rẹ̀ sì lọ kúrò.

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 18