35. Ṣé Sádókù àti Ábíátarì àwọn àlùfáà wà níbẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀? Yóò sì ṣe, ohunkóhùn tí ìwọ bá gbọ́ láti ilé ọba wá, ìwọ ó sì sọ fún Sádókù àti Ábíátarì àwọn àlùfáà.
36. Wò ó, àwọn ọmọ wọn méjèèjì sì wà níbẹ̀ pẹ̀lú wọn, Áhímásì ọmọ Sádókù, àti Jónátánì ọmọ Ábíátárì; láti ọwọ́ wọn ni ẹ̀yín ó sì rán ohùnkóhun tí ẹ̀yín bá gbọ́ sí mi.”
37. Húsáì ọ̀rẹ́ Dáfídì sì wá sí ìlú, Ábúsálómù sì wá sí Jérúsálẹ́mù.