Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 11:9-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Ṣùgbọ́n Ùráyà sun l'ẹ́nu ọ̀nà ilé ọba lọ́dọ̀ gbogbo ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.

10. Nígbà tí wọ́n sì sọ fún Dáfídì pé, “Ùráyà kò sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀,” Dáfídì sì wí fún Ùráyà pé, “Ṣebí ọ̀nà àjò ni ìwọ ti wá? Èé ha ti ṣe tí ìwọ kò fi sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ.”

11. Ùráyà sì wí fún Dáfídì pé, “Àpótí-ẹ̀rí, àti Ísírẹ́lì, àti Júdà jókòó nínú àgọ́; àti Jóábù olúwa mi, àti àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi wà ní ibùdó ní pápá: èmi ó ha lọ sí ilé mi, láti jẹ ati lati mu, àti láti bá obìnrin mi sùn? Bí ìwọ bá wà láàyè, àti bí ẹ̀mí rẹ́ si ti ń bẹ láàyè, èmi kì yóò ṣe nǹkan yìí.”

12. Dáfídì sì wí fún Ùráyà pé, “Ṣì dúró níhìn ín lónìí, lọ́la èmi ó sì jẹ́ kí ìwọ ó lọ.” Ùráyà sì dúró ní Jérúsálẹ́mù ní ọjọ́ náà, àti ijọ́ kejì.

13. Dáfídì sì pè é, ó sì jẹ, ó sì mú nítorí rẹ̀; ó sì mu kí ọtí pa á; òun sì jáde ní alẹ́ lọ sí ibùsùn rẹ̀ lọ́dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì sọ̀kalẹ́ lọ sí ilé rẹ̀.

14. Ó sì ṣe ní òwúrọ̀, Dáfídì sì kọ̀wé sí Jóábù, ó fi rán Ùráyà.

15. Ó sì kọ sínú ìwé pé, “Fi Ùráyà ṣíwájú ibi tí ogun gbé le, kí ẹ sì fà sẹ́yìn, kí wọn lè kọ lù ú, kí ó sì kú.”

16. Ó sì ṣe nígbà tí Jóábù ṣe àkíyèsí ìlú náà, ó sì yan Úráyà sí ibi kàn ní ibi tí òun mọ̀ pé àwọn alágbára ọkùnrin ń bẹ níbẹ̀.

17. Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì jáde wá, wọ́n sì bá Jóábù jà: díẹ̀ sì ṣubú nínú àwọn ènìyàn náà nínú àwọn ìránṣẹ́ Dáfídì, Ùráyà ará Hítì sì kú pẹ̀lú.

18. Jóábù sì ránṣẹ́ ó sì ro gbogbo nǹkan ogun náà fún Dáfídì.

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 11