Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 11:2-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Ó sì ṣe, ní ìgbà àṣálẹ́ kan, Dáfídì sì díde ní ibùsùn rẹ̀, ó sì ń rìn lórí òrùlé ilé ọba, láti orí òrùlé náà ni ó sì rí obìnrin kan tí ó ń wẹ̀ ara rẹ̀; obìnrin náà sì ṣe arẹwà lójú láti wò.

3. Dáfídì sì ránṣẹ́ ó sì béèrè obìnrin náà. Ẹnìkan sì wí pé, Èyí ha kọ́ ni Báṣébà, ọmọbìnrin Élíámì, aya Úráyà ará Hítì.

4. Dáfídì sì rán àwọn ìránṣẹ́, ó sì mú un; ó sì wọ inú ilé tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bá a dàpọ̀: nígbà tí ó sì wẹ ara rẹ̀ mọ́ tán, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀.

5. Obìnrin náà sì lóyún, ó sì ránṣẹ́ ó sì sọ fún Dáfídì, ó sì wí pé, “Èmi lóyún.”

6. Dáfídì sì ránṣẹ́ sí Jóábù, pé: “Rán Ùráyà ará Hítì sí mi.” Jóábù sì rán Ùráyà sí Dáfídì.

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 11