Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 11:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Lẹ́yìn ìgbà tí ọdún yípo, ní àkókò ìgbà tí àwọn ọba náà ń jáde ogun, Dáfídì sì rán Jóábù, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, àti gbogbo Ísírẹ́lì; wọ́n sì pa àwọn ọmọ Ámónì, wọ́n sì dó ti Rábà. Dáfídì sì jókòó ní Jérúsálẹ́mù.

2. Ó sì ṣe, ní ìgbà àṣálẹ́ kan, Dáfídì sì díde ní ibùsùn rẹ̀, ó sì ń rìn lórí òrùlé ilé ọba, láti orí òrùlé náà ni ó sì rí obìnrin kan tí ó ń wẹ̀ ara rẹ̀; obìnrin náà sì ṣe arẹwà lójú láti wò.

3. Dáfídì sì ránṣẹ́ ó sì béèrè obìnrin náà. Ẹnìkan sì wí pé, Èyí ha kọ́ ni Báṣébà, ọmọbìnrin Élíámì, aya Úráyà ará Hítì.

4. Dáfídì sì rán àwọn ìránṣẹ́, ó sì mú un; ó sì wọ inú ilé tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bá a dàpọ̀: nígbà tí ó sì wẹ ara rẹ̀ mọ́ tán, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀.

5. Obìnrin náà sì lóyún, ó sì ránṣẹ́ ó sì sọ fún Dáfídì, ó sì wí pé, “Èmi lóyún.”

6. Dáfídì sì ránṣẹ́ sí Jóábù, pé: “Rán Ùráyà ará Hítì sí mi.” Jóábù sì rán Ùráyà sí Dáfídì.

7. Nígbà tí Ùráyà sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Dáfídì sì bi í léèrè báwo ni Jóábù ti ṣe àti àlàáfíà àwọn ènìyàn náà, àti bí ogun náà ti ń ṣe.

8. Dáfídì sì wí fún Ùráyà pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ, kí o sì wẹ ẹṣẹ̀ rẹ.” Ùráyà sì jáde kúrò ní ilé ọba, oúnjẹ láti ọ̀dọ̀ ọba wá sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.

9. Ṣùgbọ́n Ùráyà sun l'ẹ́nu ọ̀nà ilé ọba lọ́dọ̀ gbogbo ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 11