Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 1:9-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. “Nígbà náà ó wí fún mi pé, ‘Dúró lórí ì mi kí o sì pa mí! Èmi wà nínú ìrora ikú, ṣùgbọ́n mo wà láàyè.’

10. “Nígbà náà, mo dúró lórí i rẹ̀, mo sì pa á nítorí mo mọ̀ wí pé, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣubú, kò le è yè mọ́. Mo sì mú adé tí ó wà lórí rẹ̀, idẹ tí ó wà ní apá a rẹ̀, mo sì kó wọn wá síbí fún Olúwa mi.”

11. Nígbà náà ni, Dáfídì àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, di aṣọ wọn mú, wọ́n sì fà á ya.

12. Wọ́n ṣọ̀fọ̀, wọ́n sì sunkún, wọ́n sì gbààwẹ̀ títí di ìrọ̀lẹ́ fún Ṣọ́ọ̀lù àti ọmọ rẹ̀ Jónátanì àti fún àwọn ọmọ ogun Olúwa, àti fún àwọn ilé Ísírẹ́lì, nítorí wọ́n ti ṣubú nípa idà.

13. Dáfídì sọ fún ọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún un pé, “Níbo ni ó ti wá?”O dáhùn pé, “Ọmọ àlejò ni mo jẹ́, ará Ámálékì.”

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 1