Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 6:2-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Jẹ́ kí àwa kí ó lọ sí Jọ́dánì, ní ibi tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ti le rí ọ̀pá kan, jẹ́ kí àwa kí ó kọ́lé síbẹ̀ fún wa láti gbé.”Ó sì wí pé, “lọ.”

3. Nígbà náà ni ọ̀kan lára wọn wí pé, “Ṣé ìwọ kò ní jọ̀wọ́ wa pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ?”“Èmi yóò lọ,” Èlíṣà dá a lóhùn.

4. Ó sì lọ pẹ̀lú wọn.Wọ́n sì lọ sí Jọ́dánì wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gé igi

5. Bí ọ̀kan ṣe gé igi náà, àáké irin náà bọ́ sínú omi, ó kí gbe sókè pé, o! Olúwa mi, “mo yá a ni”

6. Ènìyàn Ọlọ́run sì béèrè pé, “Níbo ni ó bọ́ sí?” Nígbà tí ó fi ibẹ̀ hàn án, Èlíṣà ge igi kan ó sì jù ú síbẹ́, ó sì mú irin náà fò lójú omi.

7. Ó wí pé, “Gbé e jáde” Nígbà náà ọkùnrin náà na ọwọ́ rẹ̀ jáde ó sì mú un.

8. Nísinsìn yìí ọba Árámù ó wà ní ogun pẹ̀lú Ísírẹ́lì ó sì bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ gbérò, ó wí pé “Èmi yóò ṣe ibùdó mi sí ibí yìí nínú èyí náà àti bí ibí yìí.”

Ka pipe ipin 2 Ọba 6