Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 25:26-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

26. Nítorí èyí, gbogbo àwọn ènìyàn láti ẹni kékeré títí dé ẹni ńlá, àti pẹ̀lú àwọn olórí ogun, sá lọ si Éjíbítì nítorí ẹ̀rù àwọn ará Bábílónì.

27. Ní ọdún kẹtàdínlógójì tí a lé Jéhóíákínì ọba Júdà kúrò nílú, ní ọdún tí Efili-Méródákì di ọba Bábílónì, ó tú Jéhóíákínì kúrò nínú túbú ní ọjọ́ kẹtàdínlógbọ̀n oṣú kéjìlá.

28. Ó sì sọ̀rọ̀ dáradára ó sì fún ún ní ìjòkòó tí ó ga lọ́lá jùlọ ju gbogbo àwọn ọba tó kù tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ní Bábílónì lọ,

29. Bẹ́ẹ̀ ni Jéhóíákínì fi sí ẹ̀gbẹ́ kan àwọn aṣọ́ túbú àti fún gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀ tí ó ku oúnjẹ ó ń jẹ, nígbà gbogbo ní orí tabílì ọba.

30. Ní ojoojúmọ́ ọba fún Jéhóíákínì ní ohun tí ó yọ̀ǹda nígbà kúgbà gẹ́gẹ́ bí ó tí ń bẹ láàyè.

Ka pipe ipin 2 Ọba 25