1. Mánásè jẹ́ ẹni ọdún méjìlá nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ìjọba, ó sì jọba ní Jérúsálẹ́mù fún ọdún márùndínlọ́gọ́ta (55). Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Héfisíbà.
2. Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, ó sì tẹ̀lé iṣẹ́ ìríra tí àwọn orílẹ̀ èdè tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.
3. Ó sì tún ibi gíga tí baba rẹ̀ Hesekíáyà tí ó parun kọ́. Ó sì tún gbé pẹpẹ dìde fún Báálì ó sì ṣe ère-òrìṣà, gẹ́gẹ́ bí Áhábù ọba Ísírẹ́lì ti ṣe. Ó sì tẹríba sí gbogbo ogun ọ̀run, ó sì ń sìn wọ́n.
4. Ó sì kọ́ pẹpẹ nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa, èyí tí Olúwa ti sọ pé, “Ní Jérúsálẹ́mù ni èmi yóò kọ orúkọ mi sí.”