Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 17:15-33 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Wọ́n kọ̀ ìlànà rẹ̀ àti májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú baba wọn àti ìkìlọ̀ tí ó ti fi fún wọn. Wọ́n tẹ̀lé òrìṣà aláìníláárí, àwọn fún rara wọn sì jẹ́ aláìníláárí. Wọ́n tẹ̀lé orílẹ̀ èdè tí ó yí wọn ká bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti kìlọ̀ fún wọn pé, “Má ṣe ṣe gẹ́gẹ́ bí wọn tí ń ṣe,” wọ́n sì ṣe ohun tí Olúwa ti kà léèwọ̀ fún wọn láti ṣe.

16. Wọ́n kọ̀ gbogbo òfin Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀ wọ́n sì ṣe òrìṣà méjì fún ara wọn, wọ́n sì gbée sí ọkàn ẹ̀gbọ̀rọ̀ màlúù, àti ère òrìṣà sí ọkàn. Wọ́n sì tẹrí wọn ba sí gbogbo ogun ọ̀run, wọ́n sì sin Báálì.

17. Wọ́n sì fi àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn rúbọ nínú iná. Wọ́n sì n fọ̀ àfọ̀sẹ, wọ́n sì ń ṣe àlùpàyídà wọ́n sì ta ara wọn láti ṣe ohun búburú níwájú Olúwa, wọ́n sì mú-un bínú.

18. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì bínú gídígídí pẹ̀lú Ísírẹ́lì ó sì mú wọn kúrò níwájú rẹ̀. Èyà Júdà nìkan ṣoṣo ni ó kù,

19. Àti pẹ̀lú, Júdà kò pa òfin Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Wọ́n tẹ̀lé ìhùwàsí àwọn Ísírẹ́lì tí wọ́n ṣe.

20. Nítorí náà Olúwa kọ gbogbo àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì; ó sì jẹ wọ́n níyà. Ó sì fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn olè tí tí tí ó fi ta wọ́n nù kúrò níwájú rẹ̀.

21. Nígbà tí ó ta Ísírẹ́lì kúrò láti ìdílé Dáfídì, wọ́n sì mú Jéróbámù ọmọ Nébátì jẹ ọba wọn. Jéróbóámù sì mú kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì yípadà kúrò ní tí tẹ̀lé Olúwa, ó sí mú kí wọn dẹ́sẹ̀ ńlá.

22. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì forítìí nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ Jéróbámù kò sì yí padà kúrò lọ́dọ̀ wọn

23. Títí tí Olúwa fi mú wọn kúrò níwájú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ó ti paláṣẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ wòlíì. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn Ísírẹ́lì mú wọn kúrò ní ilẹ̀ wọn lọ sí Iṣánṣà ni Ásíríà.

24. Ọba Ásíríà mú àwọn ènìyàn láti Bábílónì, Kútà, Áfà, Hámátì àti Ṣéfáfáímù wọ́n sì dúró ní ìlú Ṣamáríà láti rọ́pò àwọn ará Ísírẹ́lì. Wọ́n sì ń gbé ní ìlú náà.

25. Nígbà tí wọ́n gbé bẹ́ ẹ ní àkọ́kọ́, wọn kò sì bẹ̀rù Olúwa, Bẹ́ẹ̀ ni ó rán kìnnìún sí àárin wọn. Wọ́n sì pa nínú wọn.

26. Wọ́n sì sọ fún ọba Ásíríà pé: “Àwọn ènìyàn tí ìwọ lé kúrò tí o sì fi sínú ìlú Ṣamáríà kò mọ ohun tí Olúwa ìlú náà béèrè. Ó sì ti rán kìnnìún sí àárin wọn, tí ó sì ń pa wọ́n run, nítorí ènìyàn wọn kò mọ ohun tí ó béèrè.”

27. Nígbà náà ọba Ásíríà pàṣẹ yìí wí pé, “Mú ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ó mú láti Ṣamáríà lọ padà gbé níbẹ̀ kí ó sì kọ́ àwọn ènìyàn ní, ohun tí Olúwa ilẹ̀ náà béèrè.”

28. Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ó ti kúrò ní Samáríà wá gbé ní Bétélì ó sì kọ́ wọn bí a ti ń sin Olúwa.

29. Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, olúkúlùkù orílẹ̀ èdè ṣe òrìṣà tirẹ̀ ní gbogbo ìlú níbi tí wọ́n gbé wà, wọ́n sì gbé wọn nínú ilé òrìṣà àti àwọn ènìyàn Ṣamáríà ó sì ṣe wọ́n sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì.

30. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin láti Bábílónì ṣe àgọ́ àwọn wúndíá, àwọn ọkùnrin láti Kútì ṣe Négálì, àti àwọn ènìyàn láti Hámátì ṣe Áṣímà;

31. Àti àwọn ará Áfà ṣe Nébíhásì àti Tárítakì, àti àwọn ará Ṣéfárífáímù ṣun àwọn ọmọ wọn níná gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí Adiramélékì àti Anamélékì, àwọn òrìṣà Ṣéfárfáímù.

32. Wọ́n sin Olúwa, ṣùgbọ́n wọ́n sì tún yan gbogbo ẹgbẹ́ tí ènìyàn wọn láti ṣe iṣẹ́ oyè fún wọn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà ní ibi gíga.

33. Wọ́n sin Olúwa ṣùgbọ́n wọ́n sin òrìṣà wọn ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú àṣà orílẹ̀ èdè wọn láti ibi tí wọ́n ti gbé wọn wá.

Ka pipe ipin 2 Ọba 17