Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 8:1-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Lẹ́yìn ogún ọdún lásìkò ìgbà tí Sólómónì kọ́ ilé Olúwa àti ilé òun fúnrarẹ̀.

2. Sólómónì tún ìlú tí Hírámù ti fi fún un kọ́, ó sì kó àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jọ níbẹ̀ kí wọn kí ó lè máa gbé nínú ibẹ̀.

3. Nígbà náà Sólómónì lọ sí Hámátì Sóbà ó sì borí rẹ̀.

4. Ó sì tún kọ́ Tádímórì ní ihà àti gbogbo ìlú ìsúra tí ó ti kọ́ ní Hámátì.

5. Ó sì tún kọ́ òkè Bẹti Hórónì àti ìsàlẹ̀ Bétì Hórónì gẹ́gẹ́ bí ìlú olódi, pẹ̀lú ògiri àti pẹ̀lú ìlẹ̀kùn àti ọ̀pá-ìdábùú.

6. Àti gẹ́gẹ́ bí Bálátì àti gbogbo ìlú Ìṣúra, àti gbogbo ìlú fún kẹ̀kẹ́ rẹ̀ àti fún àwọn ẹsin rẹ̀ ohunkóhun tí ó bá yẹ ní kókó ní Jérúsálẹ́mù, ní Lẹ́bánónì àti ní gbogbo àyíká agbégbé tí ó ń darí.

7. Gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kúrò láti ara àwọn ará Hítì, ará Ámórò, ará Pérísì, ará Hífì àti ará Jébúsì (Àwọn ènìyàn wọ̀nyí wọn kì í ṣe àwọn ará Ísírẹ́lì),

8. Èyí ni wí pé, àwọn ọmọ wọn tí ó kù sílé ní ilẹ̀ náà, tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kò parun àwọn ni Sólómónì bu iṣẹ́ ìrú fún títí di òní yìí.

9. Ṣùgbọ́n Solómónì kò mú ọmọ ọ̀dọ̀ lára àwọn ọmọ Ísírẹ́lì fún Ísírẹ́lì, wọn jẹ́ ọ̀gágun rẹ̀, olùdarí àwọn oníkẹ̀kẹ́ àti olùdarí kẹ̀kẹ́.

10. Wọ́n sì tún jẹ́ olórí alásẹ fún ọba Sólómónì àádọ́ta ó lé nígba àwọn alákòóso lórí àwọn ènìyàn (250).

Ka pipe ipin 2 Kíróníkà 8