10. Ní àmọ́dún, ọba Nebukadínsárì ránsẹ́ síi ó sì mú-un wá sí Bábílónì, pẹ̀lú ohun èlò dáradára láti ilé Olúwa, ó sì mú arákùnrin Jehóíákínì, Sedekíà, jọba lórí Júdà àti Jérúsálẹ́mù.
11. Sedekíáyà sì jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlèlógún. Nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jérúsálẹ́mù fún ọdún mọ́kànlá.
12. Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ ko si rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú Jeremíà wòlíì, ẹni tí ó sọ̀rọ̀ Olúwa.