Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 36:1-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú Jehóáhásì ọmọ Jósíà wọn sì fi jẹ ọba ní Jérúsálẹ́mù ni ipọ̀ Baba rẹ̀.

2. Jehóáhásì sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́talélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ni Jérúsálẹ́mù fún ọdún mẹ́ta.

3. Ọba Éjíbítì lé e kúrò lórí ìtẹ́ ní Jérúsálẹ́mù ó sì bù fún un lórí Júdà, ọgọ́rún talẹ́ńtì fàdákà (100) àti talẹ́ntì wúrà kan.

4. Ọba Éjíbítì sì mú Élíákímù, arákùnrin Jehóáhásì, jẹ ọba lórí Júdà àti Jérúsálẹ́mù, ó sì yí orúkọ Eliákímù padà sí Jéhóíákíámù, ṣùgbọ́n Nékò mú arákùnrin Eliákímù, Jehóáhásì ó sì gbé e lórí Éjíbítì.

5. Jéhóíákímù sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jérúsálẹ́mù fún ọdún méjìlá. Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.

6. Nebukadínésárì ọba Bábílónì sì mú un, ó sì dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n láti mú-un lọ sí Bábílónì.

7. Nebukadínésárì pẹ̀lú mú-un lọ sí Bábílónì, ohun èlò láti ilé Olúwa, ó sì mú wọn lọ sí ààfin tirẹ̀ níbẹ̀.

8. Ìyòókù isẹ́ ìjọba Jéhóíákíámù, àwọn ohun ìríra tí ó ṣe àti gbogbo ohun tí a rí nípa rẹ̀, ni a kọ sínú ìwé àwọn ọba Ísírẹ́lì àti Júdà. Jéhóíákínì ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

9. Jehóiakínì sì jẹ́ ẹni ọdún méjìdínlógún (18) nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ́ ọba ní Jérúsálẹ́mù fún oṣù mẹ́ta àti ijọ́ mẹ́wàá ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa.

10. Ní àmọ́dún, ọba Nebukadínsárì ránsẹ́ síi ó sì mú-un wá sí Bábílónì, pẹ̀lú ohun èlò dáradára láti ilé Olúwa, ó sì mú arákùnrin Jehóíákínì, Sedekíà, jọba lórí Júdà àti Jérúsálẹ́mù.

11. Sedekíáyà sì jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlèlógún. Nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jérúsálẹ́mù fún ọdún mọ́kànlá.

12. Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ ko si rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú Jeremíà wòlíì, ẹni tí ó sọ̀rọ̀ Olúwa.

Ka pipe ipin 2 Kíróníkà 36