Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 33:4-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ó kọ́ àwọn pẹpẹ sínú ilé Olúwa ní èyí tí Olúwa ti wí pé “Orúkọ mi yóò wà ní Jérúsálẹ́mù títí láé.”

5. Nínú ààfin méjèèje ti ilé Olúwa, ó kọ́ àwọn pẹpẹ fún gbogbo àwọn ogun ọ̀run

6. Ó fi àwọn ọmọ rẹ̀ rúbọ nínú iná ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Bẹni-Hínómù, ó ń ṣe oṣó, àfọ̀ṣẹ, ìsàjẹ́ pẹ̀lú bíbéèrè lọ́dọ̀ àwọn abókúsọ̀rọ̀, àti ẹlẹ́mìí. O se ọ̀pọ̀ ohun búburú ní ojú Olúwa láti mú un bínú.

7. Ó mú ère gbígbẹ́ tí ó ti gbẹ́ ó sì gbé e sínú ilé Olúwa, ní èyí tí Ọlọ́run ti sọ fún Dáfídì àti sí ọmọ rẹ̀ Solómónì, “Nínú ilé Olúwa yìí àti ní Jérúsálẹ́mù, tí mo ti yàn kúrò nínú gbogbo àwọn ẹ̀yà Ísírẹ́lì, èmi yóò fi orúkọ mi síbẹ̀ títí láé.

8. Èmi kì yóò jẹ́ kí ẹsẹ̀ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì fi ilẹ̀ tí a yàn fún àwọn baba ńlá yín tí wọ́n bá ṣe pẹ̀lẹ́ láti ṣe gbogbo ohun tí mo palásẹ fún wọn. Nípa gbogbo àwọn òfin, àsẹ àti àwọn ìlànà tí a fún yín ní pasẹ̀ Mósè.”

9. Ṣùgbọn Mánásè mú kí Júdà àti àwọn tí ń gbé Jérúsálẹ́mù yapa, àti láti ṣe búburú ju àwọn orílẹ̀-èdè lọ, àwọn tí Olúwa ti parun níwájú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.

10. Ọlọ́run bá Mánásè sọ̀rọ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò kọbi ara sí i

Ka pipe ipin 2 Kíróníkà 33