Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 30:9-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Nítorí bí ẹ̀yin bá tún yípadà sí Olúwa, àwọn arákùnrin yín, àti àwọn ọmọ yín, yóò rí àánú níwájú àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, kí wọn kí ó lè tún padà wá sí ilẹ̀ yí: nítorí Olúwa Ọlọ́run yín, oníyọ́nú àti aláàánú ni, kì yóò sì yí ojú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ yín, bí ẹ̀yin bá padà sọ́dọ̀ rẹ̀.”

10. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn onísẹ́ náà kọjá lati ìlú dé ìlú, ní ilẹ̀ Éfúráímù àti Mánásè títí dé Sébúlúnì: Ṣùgbọ́n wọ́n fi wọ́n rẹ́rín ẹlẹ́yà, wọ́n sì gàn wọ́n.

11. Síbẹ̀ òmíràn nínú àwọn ènìyàn Áṣérì àti Mánásè àti Sébúlúnì rẹ̀ ara wọn sílẹ̀, wọ́n sì wá sí Jérúsálẹ́mù.

12. Ní Júdà pẹ̀lú, ọwọ́ Ọlọ́run wá láti fún wọn ní ọkàn kan láti pa òfin ọba mọ́ àti tí àwọn ìjòyè, nípa ọ̀rọ̀ Olúwa.

13. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn sì péjọ ní Jérúsálẹ́mù, láti pa àjọ àkàrà aláìwú mọ́ ní oṣù kejì.

14. Wọ́n sì dìde, wọ́n sì kó gbogbo pẹpẹ tí ó wà ní Jérúsálẹ́mù lọ, àti gbogbo pẹpẹ tùràrí ni wọ́n kó lọ, wọ́n sì dà wọ́n sí odò Kídírónì.

15. Nígbà náà ni wọ́n pa ẹran ìrékọjá náà ní ọjọ́ kẹ́rinlà oṣù kejì: ojú sì ti àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Léfì, wọ́n sì yà ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì mú ẹbọ sísun wá sínú ilé Olúwa.

Ka pipe ipin 2 Kíróníkà 30