Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 21:11-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Júdà. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jérúsálẹ́mù ó se àgbérè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.

12. Jóhórámì gba ìwé láti ọwọ́ Èlíjà wòlíì, tí ó wí pé:“Èyí ní ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba à rẹ Dáfídì wí: ‘Ìwọ kò tí ì rìn ní ọ̀nà àwọn baba à rẹ Jèhóṣáfátì tàbí Ásà ọba Júdà.

13. Ṣùgbọ́n ìwọ ti rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Ísírẹ́lì, ìwọ sì ti tọ́ Júdà àti àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì láti ṣe àgbèrè sí ara wọn, gẹ́gẹ́ bí ilé Áhábù ti ṣe. Ìwọ sì ti pa àwọn arákùnrin rẹ, ẹ̀yà ara ilé bàbá à rẹ, àwọn ọkùnrin tí ó dára jù ọ́ lọ.

14. Bẹ́ẹ̀ ni nísinsìn yìí, Ọlọ́run ti fẹ́rẹ́ lu àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun tí ó jẹ́ tìrẹ, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-àrùn ńlá.

15. Ìwọ tìkalára yóò ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú Àìsàn lílọ́ra ti ìfun, títí tí àìsàn náà yóò fi jẹ́ kí àwọn ìfun rẹ jáde sí ìta.’ ”

16. Olúwa ru ìbínú àwọn, ará Fílístínì àti àwọn Árábù tí wọ́n ń gbé ní Ẹ̀bá àwọn ará Kúsì.

Ka pipe ipin 2 Kíróníkà 21