Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 16:11-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Àwọn iṣẹ́ ìjọba Ásà, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni akọ sínú ìwé ọba Júdà àti Ísírẹ́lì.

12. Ní ọdún kọkàndínlógójì (39) ìjọba rẹ̀, Ásà sì ṣe àìsàn pẹ̀lú àrùn nínú ẹsẹ̀ rẹ̀. Lákókò àrùn rẹ̀ ó múná, kó dà nínú àìsàn rẹ̀ kò wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ àwọn oníṣègùn nìkan.

13. Nígbà náà tí ó pé ọdún kọ́kànlélógójì rẹ̀, Ásà kú, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn ìjọba baba rẹ̀,

14. Wọ́n sì sin ín sínú ìsà òkú tí ó ti gbé jáde fún ara rẹ̀ ní ìlú Dáfídì. Wọ́n sì tẹ sí orí àkéte tí ó fi òórùn dìdùn kún, àti onírúurú tùràrí tí a fi ọgbọ́n àwọn alápòlù pèsè, wọ́n sì ṣe ìjóná ńlá nínú ọlá ńlá rẹ̀.

Ka pipe ipin 2 Kíróníkà 16