Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 13:11-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Ní àràárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́, wọ́n gbé ọrẹ sísun àti tùràrí olóòórùn dídùn síwájú Olúwa. Wọ́n gbé àkàrà jáde sórí tábìlì àsè mímọ́, wọ́n sì tan iná sí àwọn fìtílà lórí ìdúró ọ̀pá fìtílà wúrà ní gbogbo ìrọ̀lẹ́. A ń pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa mọ́. Ṣùgbọ́n ìwọ ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀.

12. Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa; òun ni olórí wa. Àwọn àlùfáà rẹ̀ pẹ̀lú fèrè wọn yóò dún dídùn ogun sí i yín. Ẹyin ọkùnrin Ísírẹ́lì, Ẹ má ṣe dojú ìjà kọ Olúwa Ọlọ́run baba a yín nítorí ẹ̀yin kì yóò yege.”

13. Nísinsìn yìí, Jéróbóámù ti rán àwọn ọ̀wọ́ ogun lọ yíká láti jagun ẹ̀yìn. Kí ó lè jẹ́ pé, tí òun bá wà ní wájú Júdà, bíba ní bùba á wà ní ẹ̀yìn wọn.

14. Nígbà tí Júdà sì bojúwo ẹ̀yìn, sì kíyèsi i, ogun ń bẹ níwáju àti lẹ́yìn, wọn sì ké pe Olúwa, àwọn àlùfáà sì fun ìpè

Ka pipe ipin 2 Kíróníkà 13