Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 1:11-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Ọlọ́run wí fún Solómónì pé, “Níwọ̀n ìgbà tí ó jẹ́ pé ìfẹ́ ọkàn rẹ nìyí, tí ìwọ kò sì béèrè, fún ọrọ̀, ọlá tàbí ọ̀wọ̀, tàbí fún ikú àwọn ọ̀ta rẹ, àti nígbà tí ìwọ kò ti béèrè fún ẹ̀mí gígùn, ṣùgbọ́n tí ìwọ béèrè fún ọgbọ́n àti ìmọ̀ láti ṣàkóso àwọn ènìyàn mi tí èmi fi ọ́ jẹ ọba lé lórí,

12. Nítorí náà, ọgbọ́n àti ìmọ̀ ni a ó fi fún ọ, Èmi yóò sì fún ọ ní ọrọ̀, ọlá àti ọ̀wọ̀, irú èyí tí ọba ti ó wà ṣáájú rẹ kò ní, tí àwọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn rẹ kò sì ní ní irú rẹ̀.”

13. Nígbà náà ni Sólómónì sì ti ibi gígá Gíbíónì lọ sí Jérúsálẹ́mù láti iwájú àgọ́ ìpàde. Ó sì jọba lórí Ísírẹ́lì.

14. Sólómónì kó kẹ̀kẹ́ àti ẹsin jọ, ó sì ní ẹgbàáje kẹ̀kẹ́ àti ẹgbàafà ẹlẹ́sin, tí ó kó pamọ́ sí ìlú kẹ̀kẹ́ àti pẹ̀lú rẹ̀ ni Jérúsálẹ́mù

15. ọba náà ṣe fàdákà àti wúrà gẹ́gẹ́ bí ó ti wọ́pọ̀ ní Jérúsálẹ́mù bí òkúta, àti Kédárì ó pọ̀ bí igi Síkámórè ní àwọn ẹsẹ̀ òkè.

16. Àwọn ẹsin Sólómónì ní a gbà láti ìlú òkèrè Éjíbítì àti láti kúè oníṣòwò ti ọba ni ó rà wọ́n láti Kúè.

17. Wọ́n ra kẹ̀kẹ́ kan láti Éjíbítì. Fún ọgọ́rùn ún mẹ́fà Sékélì (6,000) fàdákà àti ẹṣin kan fún ọgọ́rin-méjì-ó-dínláàdọ́ta. Wọ́n ko wọn lọ sọ́dọ̀ àwọn ọba mìíràn ti Hítì àti ti àwọn ará Árámíà.

Ka pipe ipin 2 Kíróníkà 1