1. Lẹ́yìn ìgbà tí àwọn Fílístínì ti gba àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run lọ, wọ́n gbé e láti Ebenésérì sí Ásídódù.
2. Wọ́n gbé àpótí ẹ̀rí náà lọ sí Tẹ́ḿpìlì Dágónì, wọ́n gbé e kalẹ̀ sí ẹ̀gbẹ́ Dágónì.
3. Nígbà tí àwọn ará Ásídódù jí ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ní ọjọ́ kejì, Dágónì ṣubú, ó dojúbolẹ̀ níwájú àpótí Olúwa, wọ́n sì gbé Dágónì, wọ́n tún fi sí ààyè rẹ̀.