Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 4:8-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Àwa gbé! Ta ni yóò gbà wá kúrò lọ́wọ́ Ọlọ́run alágbára yìí? Àwọn ni Ọlọ́run tí ó fi ìpọ́njú pa àwọn ará Éjíbítì pẹ̀lú gbogbo àjàkálẹ̀-àrùn ní ihà.

9. Ẹ jẹ́ alágbára Fílístínì, ẹ ṣe bí ọkùnrin, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ̀yin yóò di ẹrú àwọn Hébérù, bí wọ́n ti jẹ́ sí i yín: Ẹ jẹ́ alágbára ọkùnrin, kí ẹ sì jagun!”

10. Nígbà náà àwọn Fílístínì jà, wọ́n sì ṣẹ́gun àwọn Ísírẹ́lì olúkúlùkù sì sá padà sínú àgọ́ rẹ̀, wọ́n pa ọ̀pọ̀ ènìyàn; Àwọn ará Ísírẹ́lì tí ó kú sí ogun sì jẹ́ ẹgbàámẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọmọ ogun orí ilẹ̀ (30,000).

11. Wọ́n gba àpótí ẹ̀rí Olúwa, àwọn ọmọkùnrin Élì méjèèjì sì kú, Hófínì àti Fínéhásì.

12. Lọ́jọ́ kan náà tí ará Bẹ́ńjámínì kan sá wá láti ojú ogun tí ó sì lọ sí Ṣílò, aṣọ rẹ̀ sì fàya pẹ̀lú eruku lórí rẹ̀.

13. Nígbà tí ó sì dé, Élì sì jókòó sórí àga rẹ̀ ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà, ó ń wò, ọkàn rẹ̀ kò balẹ̀ nítorí àpótí ẹ̀rí Olúwa. Nígbà tí ọkùnrin náà wọ ìlú tí ó sì sọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀, gbogbo ìlú bẹ̀rẹ̀ sí sunkún

14. Élì gbọ́ ìró ohùn ẹkún náà ó sì béèrè pé, “Kí ni ìtúmọ̀ ariwo yìí?”Ọkùnrin náà sì sáré tọ Élì wá

15. ẹni tí ó jẹ́ ẹni méjìdínlọ́gọ́run ọdún, tí ojú rẹ̀ kò sì ríran mọ́.

16. Ọkùnrin náà sọ fún Élì, “Mo ṣẹ̀ ṣẹ̀ dé láti ibi ogun náà ni: mo sá láti ibi ogun náà wá lónìí.”Élì sì béèrè pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀ ọmọ mi?”

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 4