Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 4:6-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Ní ìgbà tí àwọn Fílístínì gbọ́ ariwo náà wọ́n béèrè pé, “Kí ni gbogbo ariwo yìí ní ibùdó Hébérù?”Nígbà tí wọ́n mọ̀ wí pé àpótí ẹ̀rí Olúwa ti wá sí ibùdó,

7. Àwọn Fílístínì sì bẹ̀rù pé, Ọlọ́run kékeré ti wọ ibùdó, wọ́n wí pé, “A wọ wàhálà, irú èyí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí.

8. Àwa gbé! Ta ni yóò gbà wá kúrò lọ́wọ́ Ọlọ́run alágbára yìí? Àwọn ni Ọlọ́run tí ó fi ìpọ́njú pa àwọn ará Éjíbítì pẹ̀lú gbogbo àjàkálẹ̀-àrùn ní ihà.

9. Ẹ jẹ́ alágbára Fílístínì, ẹ ṣe bí ọkùnrin, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ̀yin yóò di ẹrú àwọn Hébérù, bí wọ́n ti jẹ́ sí i yín: Ẹ jẹ́ alágbára ọkùnrin, kí ẹ sì jagun!”

10. Nígbà náà àwọn Fílístínì jà, wọ́n sì ṣẹ́gun àwọn Ísírẹ́lì olúkúlùkù sì sá padà sínú àgọ́ rẹ̀, wọ́n pa ọ̀pọ̀ ènìyàn; Àwọn ará Ísírẹ́lì tí ó kú sí ogun sì jẹ́ ẹgbàámẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọmọ ogun orí ilẹ̀ (30,000).

11. Wọ́n gba àpótí ẹ̀rí Olúwa, àwọn ọmọkùnrin Élì méjèèjì sì kú, Hófínì àti Fínéhásì.

12. Lọ́jọ́ kan náà tí ará Bẹ́ńjámínì kan sá wá láti ojú ogun tí ó sì lọ sí Ṣílò, aṣọ rẹ̀ sì fàya pẹ̀lú eruku lórí rẹ̀.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 4