Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 4:14-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Élì gbọ́ ìró ohùn ẹkún náà ó sì béèrè pé, “Kí ni ìtúmọ̀ ariwo yìí?”Ọkùnrin náà sì sáré tọ Élì wá

15. ẹni tí ó jẹ́ ẹni méjìdínlọ́gọ́run ọdún, tí ojú rẹ̀ kò sì ríran mọ́.

16. Ọkùnrin náà sọ fún Élì, “Mo ṣẹ̀ ṣẹ̀ dé láti ibi ogun náà ni: mo sá láti ibi ogun náà wá lónìí.”Élì sì béèrè pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀ ọmọ mi?”

17. Ọkùnrin tí ó mú ìròyìn náà wá dáhùn pé, “Ísírẹ́lì sá níwájú àwọn Fílístínì, àwọn ọmọ ogun náà sì kú lọ́pọ̀lọpọ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ méjèèjì, Hófínì àti Fínéhásì, wọ́n kú, wọ́n sì ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ”

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 4