Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 4:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọ̀rọ̀ Sámúẹ́lì tọ gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì wá.Nísinsìnyìí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jáde láti lọ bá àwọn Fílístínì jà. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì pàgọ́ sí Ebenésérì àti àwọn Fílístínì ní Áfékì.

2. Àwọn Fílístínì mú ogun wọn sọ̀kalẹ̀ láti pàdé Ísírẹ́lì, nígbà tí ogun náà bẹ̀rẹ̀, àwọn Fílístínì ṣẹ́gun Ísírẹ́lì wọ́n pa ẹgbàájì ọkùnrin nínú ogun náà (4,000).

3. Nígbà tí àwọn ọmọ ogun náà padà sí ibùdó, àwọn àgbà Ísírẹ́lì sì béèrè pé, “Èéṣe ti Olúwa fi mú kí àwọn Fílístínì ṣẹ́gun wa lónìí? Ẹ jẹ́ kí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa láti Ṣílò wá, kí ó ba à le lọ pẹ̀lú wa kí ó sì gbàwá là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀ta wa.”

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 4