Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 26:9-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Dáfídì sì wí fún Ábíṣáì pé, “Má ṣe pa á nítorí pé ta ni lè na ọwọ́ rẹ̀ sí ẹni àmì-òróró Olúwa kí ó sì wà láìjẹ̀bi?”

10. Dáfídì sì wí pé, “Bí Olúwa tí ń bẹ Olúwa yóò pa á, tàbí ọjọ́ rẹ̀ yóò sì pé tí yóò kú, tàbí òun ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibi ìjà yóò sì ṣègbé níbẹ̀.

11. Olúwa má jẹ́ kí èmi na ọwọ́ mi sí ẹni àmì òróró Olúwa: ǹjẹ́ èmi bẹ̀ ọ́, mú ọ̀kọ̀ náà tí ń bẹ níbi tìmùtìmù rẹ̀, àti ìgò omi kí a sì máa lọ.”

12. Dáfídì sì mú ọ̀kọ̀ náà àti ìgò omi náà kúrò níbi tìmùtìmù Ṣọ́ọ̀lù: wọ́n sì bá tiwọn lọ, kò sì sí ẹnìkan tí ó rí i, tàbí tí ó mọ̀: kò sì sí ẹnikàn tí ó jí; gbogbo wọn sì sùn; nítorí pé oorun ìjìká láti ọdọ Olúwa wá ti ṣubú lù wọ́n.

13. Dáfídì sì rékọjá sí ìhà kejì, ó sì dúró lórí òkè kan tí ó jìnnà réré; àlàfo kan sì wà láàrin méjì wọn:

14. Dáfídì sì kọ sí àwọn ènìyàn náà àti sí Ábínérì ọmọ Nérì wí pé, “Ìwọ kò dáhùn, Ábínérì?”Nígbà náà ni Ábínérì sì dáhùn wí pé, “Ìwọ ta ni ń pe ọba?”

15. Dáfídì sì wí fún Ábínérì pé, “Alágbára ọkùnrin kọ́ ni ìwọ bí? Ta ni ó sì dàbí ìwọ ni Ísírẹ́lì? Ǹjẹ́ èéṣe tí ìwọ kò tọ́jú ọba Olúwa rẹ? Nítorí ẹnìkan nínú àwọn ènìyàn náà ti wọlé wá láti pa ọba Olúwa rẹ.

16. Nǹkan tí ìwọ ṣe yìí kò dára. Bí Olúwa ti ń bẹ, o tọ́ kí ẹ̀yin ó kú, nítorí pé ẹ̀yin kò pa olúwa yín mọ́, ẹni àmì òróró Olúwa. Ǹjẹ́ sì wo ibi tí ọ̀kọ̀ ọba gbé wà, àti ìgò omi tí ó ti wà ní bi tìmùtìmù rẹ̀.”

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 26