Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 26:7-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Bẹ́ẹ̀ ni Dáfídì àti Ábíṣáì sì tọ àwọn ènìyàn náà wá lóru: sì wò ó, Ṣọ́ọ̀lù dùbúlẹ̀ ó sì ń sùn láàrin kẹ̀kẹ́, a sì fi ọ̀kọ̀ rẹ̀ gúnlẹ̀ ni ibi tìmùtìmù rẹ̀: Ábínérì àti àwọn ènìyàn náà sì dùbúlẹ̀ yí i ká.

8. Ábíṣáì sì wí fún Dáfídì pé, “Ọlọ́run ti fi ọ̀ta rẹ lé ọ lọ́wọ́ lónìí: ǹjẹ́ èmi bẹ̀ ọ́, ṣáà jẹ́ kí èmi o fi ọ̀kọ̀ gún un mọ́lẹ̀ lẹ́ẹ̀kan, èmi kì yóò gun un lẹ́ẹ̀méjì.”

9. Dáfídì sì wí fún Ábíṣáì pé, “Má ṣe pa á nítorí pé ta ni lè na ọwọ́ rẹ̀ sí ẹni àmì-òróró Olúwa kí ó sì wà láìjẹ̀bi?”

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 26