Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 26:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà náà ni àwọn ará Sífì tọ Ṣọ́ọ̀lù wá sí Gíbéà, wọn wí pé, “Dáfídì kò ha fi ara rẹ̀ pamọ́ níbi òkè Hákílà, èyí tí ó wà níwájú Jésímónì?”

2. Ṣọ́ọ̀lù sì dìde ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ijù Sífì ẹgbẹ̀ẹ́dógún àṣàyàn ènìyàn ni Ísírẹ́lì sì pẹ̀lú rẹ̀ láti wá Dáfídì ni ijù Sífì.

3. Ṣọ́ọ̀lù sì pàgọ́ rẹ̀ ní ibi òkè Hákílà tí o wà níwájú Jésímónì lójú ọ̀nà, Dáfídì sì jókòó ni ibi ijù náà, ó sì rí pé Ṣọ́ọ̀lù ń tẹ̀lé òun ni ijù náà.

4. Dáfídì sì rán àyọ́lẹ̀wò jáde, ó sì mọ nítòótọ́ pé Ṣọ́ọ̀lù ń bọ̀.

5. Dáfídì sì dìde, ó sì wá sí ibi ti Ṣọ́ọ̀lù pàgọ́ sí: Dáfídì rí ibi tí Ṣọ́ọ̀lù gbé dúbúlẹ̀ sí, àti Ábínérì ọmọ Nérì, olórí ogun rẹ̀: Ṣọ́ọ̀lù sì dùbúlẹ̀ láàrin àwọn kẹ̀kẹ́, àwọn ènìyàn náà sì pàgọ́ wọn yí i ká.

6. Dáfídì sì dáhùn, ó sì wí fún Áhímélékì, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Hétì, àti fún Ábíṣáì ọmọ Sérúíà ẹ̀gbọ́n Jóábù, pé, “Ta ni yóò ba mi sọ̀kalẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Ṣọ́ọ̀lù ni ibùdó?”Ábíṣáì sì wí pé, “Èmi yóò ba ọ sọ̀kalẹ̀ lọ.”

7. Bẹ́ẹ̀ ni Dáfídì àti Ábíṣáì sì tọ àwọn ènìyàn náà wá lóru: sì wò ó, Ṣọ́ọ̀lù dùbúlẹ̀ ó sì ń sùn láàrin kẹ̀kẹ́, a sì fi ọ̀kọ̀ rẹ̀ gúnlẹ̀ ni ibi tìmùtìmù rẹ̀: Ábínérì àti àwọn ènìyàn náà sì dùbúlẹ̀ yí i ká.

8. Ábíṣáì sì wí fún Dáfídì pé, “Ọlọ́run ti fi ọ̀ta rẹ lé ọ lọ́wọ́ lónìí: ǹjẹ́ èmi bẹ̀ ọ́, ṣáà jẹ́ kí èmi o fi ọ̀kọ̀ gún un mọ́lẹ̀ lẹ́ẹ̀kan, èmi kì yóò gun un lẹ́ẹ̀méjì.”

9. Dáfídì sì wí fún Ábíṣáì pé, “Má ṣe pa á nítorí pé ta ni lè na ọwọ́ rẹ̀ sí ẹni àmì-òróró Olúwa kí ó sì wà láìjẹ̀bi?”

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 26