Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 25:40-44 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

40. Àwọn ìránṣẹ́ Dáfídì sì lọ sọ́dọ̀ Ábígáílì ni Kamẹ́lì, wọn sì sọ fún un pé, “Dáfídì rán wá si ọ láti mu ọ ṣe aya rẹ̀.”

41. Ó sì dìde, ó sì dojúbolẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ ó jẹ́ ìránṣẹ́ kan láti máa wẹ ẹsẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi.”

42. Ábígáílì sì yára, ó sì dìde, ó sì gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn iránṣẹ́bìnrin rẹ̀ márùnún sì tẹ̀lé e lẹ́yìn; oun sì tẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ Dáfídì, o sì wá di aya rẹ̀.

43. Dáfídì sì mú Áhínóámù ará Jésírẹ́lì; àwọn méjèèjì sì jẹ́ aya rẹ̀.

44. Ṣùgbọ́n Ṣọ́ọ̀lù ti fi Míkálì ọmọ rẹ̀ obìnrin aya Dáfídì, fún Fátíélì ọmọ Láìsi tí i ṣe ara Gálímù.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 25