Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 22:9-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Dóégì ara Édómù tí a fi jẹ olórí àwọn ìránṣẹ́ Ṣọ́ọ̀lù, sì dáhùn wí pé, “Èmi rí ọmọ Jésè, ó wá sí Nóbù, sọ́dọ̀ Áhímélékì ọmọ Áhítúbì.

10. Òun sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa fún un, ó sì fún un ní oúnjẹ́, kò sí fún un ni idà Gòláyátì ara Fílístínì.”

11. Ọba sì ránṣẹ́ pe Áhímélékì àlùfáà, ọmọ Áhítúbì àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀, àwọn àlùfáà tí ó wà ni Nóbù: gbogbo wọn ni ó sì wá sọ́dọ̀ ọba.

12. Ṣọ́ọ̀lù sì wí pé, “Ǹjẹ́ gbọ́, ìwọ ọmọ Áhítúbì.”Òun sì wí pé, “Èmi nìyìí Olúwa mi.”

13. Ṣọ́ọ̀lù sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi dìmọ̀lù sí mi, ìwọ àti ọmọ Jésè, tí ìwọ fi fún un ní àkàrà, àti idà, àti ti ìwọ fi béèré fún un lọ́dọ̀ Ọlọ́run kí òun lè dìde sí mi, láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”

14. Áhímélékì sì dá ọba lóhùn, ó sì wí pé, “Ta ni Olúwa rẹ̀ tí ó jẹ́ olóótọ́ nínú gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ bí Dáfídì, ẹni tí ó jẹ́ àna ọba, ẹni tí ó ń gbọ́ tìrẹ, tí ó sì ni ọlá ni ilé rẹ.

15. Òní l'èmi ó ṣẹṣẹ̀ máa béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run fún un bí? Kí èyí jìnnà sí mi: kí ọba má ṣe ka nǹkan kan sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́rùn, tàbí sí gbogbo ìdílé baba mi: nítorí pé ìránṣẹ́ rẹ̀ kò mọ̀kan nínú gbogbo nǹkan yìí, díẹ̀ tabi púpọ̀.”

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 22