Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 22:2-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Olúkúlùkù ẹni tí ó tí wà nínú ipọ́njú, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ti jẹ gbésè, àti olúkúlùkù ẹni tí ó wà nínú ìbànújẹ́, sì kó ara wọn jọ sọ́dọ̀ rẹ̀, òun sì jẹ́ olórí wọn; àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì tó iwọ̀n irinwó ọmọkùnrin.

3. Dáfídì sì ti ibẹ̀ náà lọ sí Mísípa tí Móábù: ó sì wí fún ọba Móábù pé, “Jẹ́ kí baba àti ìyá mi, èmi bẹ̀ ọ́ wá bá ọ gbé, títí èmi yóò fi mọ ohun ti Ọlọ́run yóò ṣe fún mi.”

4. Ó sì mú wọn wá ṣíwájú ọba Móábù; wọ́n sì bá á gbé ní gbogbo ọjọ́ tí Dáfídì fí wà nínú ihò náà.

5. Gádì wòlíì sí wí fún Dáfídì pé, “Ma ṣe gbé inú ihò náà, yẹra, kí o sí lọ sí ilẹ̀ Júdà.” Nígbà náà ni Dáfídì sì yẹra, ó sì lọ sínú igbó Hárétì.

6. Ṣọ́ọ̀lù si gbọ́ pé a rí Dáfídì àti àwọn ọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀; Ṣọ́ọ̀lù sì ń bẹ ní Gíbéà lábẹ́ igi kan ní Rámà; ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì ń bẹ lọ́wọ́ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì dúró tì í.

7. Nígbà náà ni Ṣọ́ọ̀lù wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó dúró tì í, pé, “Ǹjẹ́ ẹ gbọ́ ẹ̀yin ara Bẹ́ńjámínì, ọmọ Jésè yóò há fún olúkùlùkù yín ni oko ọgbà àjàrà bí? Kí ó sì sọ gbogbo yin dì olórí ẹgbẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún bí?

8. Tí gbogbo yín di ìmọ̀lù sí mi, tí kò sì sí ẹnìkan tí ó sọ létí mi pé, ọmọ mi ti bá ọmọ Jésè mulẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kó sì sí ẹnìkan nínú yín tí ó ṣàánú mi, tí ó sì sọ ọ́ létí mi pé, ọmọ mi mú kí ìránṣẹ́ mi dìde sí mi láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 22