Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 22:2-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Olúkúlùkù ẹni tí ó tí wà nínú ipọ́njú, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ti jẹ gbésè, àti olúkúlùkù ẹni tí ó wà nínú ìbànújẹ́, sì kó ara wọn jọ sọ́dọ̀ rẹ̀, òun sì jẹ́ olórí wọn; àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì tó iwọ̀n irinwó ọmọkùnrin.

3. Dáfídì sì ti ibẹ̀ náà lọ sí Mísípa tí Móábù: ó sì wí fún ọba Móábù pé, “Jẹ́ kí baba àti ìyá mi, èmi bẹ̀ ọ́ wá bá ọ gbé, títí èmi yóò fi mọ ohun ti Ọlọ́run yóò ṣe fún mi.”

4. Ó sì mú wọn wá ṣíwájú ọba Móábù; wọ́n sì bá á gbé ní gbogbo ọjọ́ tí Dáfídì fí wà nínú ihò náà.

5. Gádì wòlíì sí wí fún Dáfídì pé, “Ma ṣe gbé inú ihò náà, yẹra, kí o sí lọ sí ilẹ̀ Júdà.” Nígbà náà ni Dáfídì sì yẹra, ó sì lọ sínú igbó Hárétì.

6. Ṣọ́ọ̀lù si gbọ́ pé a rí Dáfídì àti àwọn ọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀; Ṣọ́ọ̀lù sì ń bẹ ní Gíbéà lábẹ́ igi kan ní Rámà; ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì ń bẹ lọ́wọ́ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì dúró tì í.

7. Nígbà náà ni Ṣọ́ọ̀lù wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó dúró tì í, pé, “Ǹjẹ́ ẹ gbọ́ ẹ̀yin ara Bẹ́ńjámínì, ọmọ Jésè yóò há fún olúkùlùkù yín ni oko ọgbà àjàrà bí? Kí ó sì sọ gbogbo yin dì olórí ẹgbẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún bí?

8. Tí gbogbo yín di ìmọ̀lù sí mi, tí kò sì sí ẹnìkan tí ó sọ létí mi pé, ọmọ mi ti bá ọmọ Jésè mulẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kó sì sí ẹnìkan nínú yín tí ó ṣàánú mi, tí ó sì sọ ọ́ létí mi pé, ọmọ mi mú kí ìránṣẹ́ mi dìde sí mi láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”

9. Dóégì ara Édómù tí a fi jẹ olórí àwọn ìránṣẹ́ Ṣọ́ọ̀lù, sì dáhùn wí pé, “Èmi rí ọmọ Jésè, ó wá sí Nóbù, sọ́dọ̀ Áhímélékì ọmọ Áhítúbì.

10. Òun sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa fún un, ó sì fún un ní oúnjẹ́, kò sí fún un ni idà Gòláyátì ara Fílístínì.”

11. Ọba sì ránṣẹ́ pe Áhímélékì àlùfáà, ọmọ Áhítúbì àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀, àwọn àlùfáà tí ó wà ni Nóbù: gbogbo wọn ni ó sì wá sọ́dọ̀ ọba.

12. Ṣọ́ọ̀lù sì wí pé, “Ǹjẹ́ gbọ́, ìwọ ọmọ Áhítúbì.”Òun sì wí pé, “Èmi nìyìí Olúwa mi.”

13. Ṣọ́ọ̀lù sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi dìmọ̀lù sí mi, ìwọ àti ọmọ Jésè, tí ìwọ fi fún un ní àkàrà, àti idà, àti ti ìwọ fi béèré fún un lọ́dọ̀ Ọlọ́run kí òun lè dìde sí mi, láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”

14. Áhímélékì sì dá ọba lóhùn, ó sì wí pé, “Ta ni Olúwa rẹ̀ tí ó jẹ́ olóótọ́ nínú gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ bí Dáfídì, ẹni tí ó jẹ́ àna ọba, ẹni tí ó ń gbọ́ tìrẹ, tí ó sì ni ọlá ni ilé rẹ.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 22