Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 19:15-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Nígbà náà ni Ṣọ́ọ̀lù rán ọkùnrin náà padà láti lọ wo Dáfídì ó sì sọ fún wọn pé, “Mú wa fún mi láti orí ibùsùn rẹ̀ kí èmi kí ó le pa á.”

16. Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkùnrin náà wọlé, ère ni ó bá lórí ibùsùn àti irun ewúrẹ́ ní orí ère náà.

17. Ṣọ́ọ̀lù wí fún Míkálì pé, “Èéṣe tí ìwọ fi tàn mí báyìí tí o sì jẹ́ kí ọ̀ta mi sálọ tí ó sì bọ́?”Míkálì sọ fún un pé, “Ó wí fún mi, jẹ́ kí èmi ó lọ. Èéṣe tí èmi yóò fi pa ọ́?”

18. Nígbà tí Dáfídì ti sá lọ tí ó sì ti bọ́, ó sì lọ sọ́dọ̀ Sámúẹ́lì ní Rámà ó sì sọ gbogbo ohun tí Ṣọ́ọ̀lù ti ṣe fún un. Òun àti Sámúẹ́lì lọ sí Náíótì láti dúró níbẹ̀.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 19