Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 14:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọjọ́ kan, Jónátanì ọmọ Ṣọ́ọ̀lù wí fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó ń ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí a rékọjá lọ sí ìlú olódi àwọn Fílístínì tí ó wà ní ìhà kejì.” Ṣùgbọ́n kò sọ fún baba rẹ̀.

2. Ṣọ́ọ̀lù sì dúró ní ìhà etí ìpínlẹ̀ Gíbéà lábẹ́ igi pòmégánétè èyí tí ó wà ní Mígírónù. Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin (600) sì wà pẹ̀lú rẹ̀,

3. lára wọn ni Áhíjà, tí ó wọ Éfódù. Òun ni ọmọ arákùnrin Íkábódù Áhítúbì, ọmọ Fínéhásì, ọmọ Élì, àlùfáà Olúwa ní Ṣílò kò sí ẹni tí ó mọ̀ pé Jónátanì ti lọ.

4. Ní ọ̀nà tí Jónátanì ti ń fẹ́ láti kọjá dé ìlú olódi àwọn Fílístínì, ní bèbè òkúta mímú kan wá, orúkọ èkíní sì ń jẹ́ Bóṣéṣì, orúkọ èkejì sì ń jẹ́ Sénè.

5. Bèbè òkúta kan dúró sí àríwá ní ìhà Míkímásì, èkejì sì wà ní gúsù ní ìhà Gíbéà.

6. Jónátanì sì wí fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó ń ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ sí ìlu olódi àwọn aláìkọlà yìí. Bóyá Olúwa yóò jà fún wa, kò sí ohun tó lè di Olúwa lọ́wọ́ láti gbàlà, yálà nípaṣẹ̀ púpọ̀ tàbí nípaṣẹ̀ díẹ̀.”

7. Ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì wí pé, “Ṣe gbogbo ohun tí ó wà ní ọkàn rẹ, tẹ̀ṣíwájú; Èmi wà pẹ̀lú ọkàn àti ẹ̀mí rẹ.”

8. Jónátanì sì wí pé, “Wá nígbà náà, àwa yóò rékọjá sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin wọ̀nyí, kí a sì jẹ́ kí wọ́n rí wa.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 14