Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 1:24-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Nígbà tí ó sì gba ọmú lẹ́nu rẹ̀, ó sì mú un gòkè lọ pẹ̀lú ara rẹ̀. Pẹ̀lú ẹgbọrọ màlúù mẹ́ta, àti ìyẹ̀fun éfà kan, àti ìgò ọti-wáìnì kan, ó sì mú un wá sí ilé Olúwa ní Ṣílò: ọmọ náà ṣì wà ní ọmọdé.

25. Wọ́n pa ẹgbọrọ màlúù, wọ́n sì mú ọmọ náà tọ Élì wá.

26. Hánà sì wí pé, “Olúwa mi, bí ọkàn rẹ ti wà láàyè, Olúwa mi, èmi ni obìnrin náà tí ó dúró lẹ́bàá ọ̀dọ̀ rẹ níhìn-ín tí ń tọrọ lọ́dọ̀ Olúwa.

27. Ọmọ yìí ni mo ń tọrọ; Olúwa sì fi ìdáhùn ìbéèrè tí mo béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ fún mi.

28. Nítorí náà pẹ̀lú, èmi fí i fún Olúwa; ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀: nítorí tí mo ti béèrè rẹ̀ fún Olúwa.” Wọn si wólẹ̀ sin Olúwa nibẹ̀.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 1