Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 9:17-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Sólómónì sì tún Gésérì kọ́, àti Bẹti Hórónì ìṣàlẹ̀,

18. Àti Bálátì àti Támárì ní ihà, láàrin rẹ̀,

19. Àti gbogbo ìlú ìṣúra tí Sólómónì ní, àti ìlú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, àti ìlú fún àwọn ẹlẹ́sin rẹ̀, àti èyí tí ó ń fẹ́ láti kọ́ ní Jérúsálẹ́mù, ní Lébánónì àti ní gbogbo ilẹ̀ ìjọba rẹ̀ tí ó ń ṣe àkóso.

20. Gbogbo ènìyàn tí ó kù nínú àwọn ará Ámórì ará Hítì, Pérísì, Hífì àti Jébúsì, àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ará Ísírẹ́lì,

21. ìyẹn ni pé àwọn ọmọ wọn tí ó kù ní ilẹ̀ náà, tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kò le parun pátapáta, àwọn ni Sólómónì bu iṣẹ́ ìrú fún títí di òní yìí.

22. Ṣùgbọ́n, Sólómónì kò fi ẹnìkankan ṣe ẹrú nínú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì; àwọn ni ológun rẹ̀ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ìjòyè rẹ̀, àti àwọn balógun rẹ̀, àti àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rẹ̀ àti ti àwọn ẹlẹ́sin rẹ̀.

23. Àwọn sì tún ni àwọn olórí olùtọ́jú tí wọ́n wà lórí iṣẹ́ Sólómónì, àádọ́tàdínlẹ́gbẹ̀ta (550), ní ń ṣe àkóso lórí àwọn ènìyàn tí ń ṣe iṣẹ́ náà.

24. Lẹ́yìn ìgbà tí ọmọbìnrin Fáráò ti gòkè láti ìlú Dáfídì wá sí ààfin tí Sólómónì kọ́ fún un, nígbà náà ni ó kọ́ Mílò.

25. Nígbà mẹ́ta lọ́dún ni Sólómónì ń rú ẹbọ ọrẹ sísun àti ẹbọ àlàáfíà lórí pẹpẹ tí ó tẹ́ fún Olúwa, ó sì sun tùràrí níwájú Olúwa pẹ̀lú wọn, bẹ́ẹ̀ ni ó parí ilé náà.

26. Sólómónì ọba sì tún ṣe òwò ọkọ̀ ní Esioni-Gébérì, tí ó wà ní ẹ̀bá Élátì ní Édómù, létí òkun pupa.

27. Hírámù sì rán àwọn ènìyàn rẹ̀, àwọn atukọ̀ tí ó mọ òkun, pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ Sólómónì.

28. Wọ́n sì dé ófírì, wọ́n sì mú irínwó ó lé ogún (420) talẹ́ǹtì wúrà, tí wọ́n ti gbà wá fún Sólómónì ọba.

Ka pipe ipin 1 Ọba 9