Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 9:16-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Fáráò ọba Éjíbítì sì ti kọlu Gésérì, ó sì ti fi iná sun ún, ó sì pa àwọn ará Kénánì tí ń gbé ìlú náà, ó sì fi ta ọmọbìnrin rẹ̀, aya Sólómónì lọ́rẹ.

17. Sólómónì sì tún Gésérì kọ́, àti Bẹti Hórónì ìṣàlẹ̀,

18. Àti Bálátì àti Támárì ní ihà, láàrin rẹ̀,

19. Àti gbogbo ìlú ìṣúra tí Sólómónì ní, àti ìlú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, àti ìlú fún àwọn ẹlẹ́sin rẹ̀, àti èyí tí ó ń fẹ́ láti kọ́ ní Jérúsálẹ́mù, ní Lébánónì àti ní gbogbo ilẹ̀ ìjọba rẹ̀ tí ó ń ṣe àkóso.

20. Gbogbo ènìyàn tí ó kù nínú àwọn ará Ámórì ará Hítì, Pérísì, Hífì àti Jébúsì, àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ará Ísírẹ́lì,

21. ìyẹn ni pé àwọn ọmọ wọn tí ó kù ní ilẹ̀ náà, tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kò le parun pátapáta, àwọn ni Sólómónì bu iṣẹ́ ìrú fún títí di òní yìí.

Ka pipe ipin 1 Ọba 9