Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 7:44-51 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

44. Agbada ńlá náà, àti màlúù méjìlá tí ó wà lábẹ́ rẹ̀;

45. Ìkòkò, ọkọ́ àti àwo kòtò.Gbogbo ohun èlò wọ̀nyí tí Hírámù ṣe fún Sólómónì ọba nítorí iṣẹ́ Olúwa sì jẹ́ idẹ dídán.

46. Ọba sì dá wọn ní ilẹ̀ amọ̀ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jọ́dánì lágbedeméjì Ṣúkótì àti Ṣárítanì.

47. Sólómónì sì jọ̀wọ́ gbogbo nǹkan wọ̀nyí láìwọ̀n, nítorí tí wọ́n pọ̀ jù; bẹ́ẹ̀ ni a kò sì mọ ìwọ̀n idẹ.

48. Sólómónì sì tún ṣe gbogbo ohun ọ̀ṣọ́ tí ń ṣe ti ilé Olúwa pẹ̀lú:pẹpẹ wúrà;tabílì wúrà lórí èyí tí àkàrà ìfihàn gbé wà;

49. Ọ̀pá fìtílà kìkì wúrà, márùn-ún ní apá ọ̀tún àti márùn ún ní apá òsì, níwájú ibi mímọ́ jùlọ; ìtànná ewéko;fìtílà àti ẹ̀mú wúrà;

50. Ọpọ́n kìkì wúrà, àlùmágàjí fìtílà, àti àwo kòtò, àti ṣíbí àti àwo tùràrí ti wúrà dáradára;àti àgbékọ́ wúrà fún ilẹ̀kùn inú ilé ibi mímọ́ jùlọ àti fún ilẹ̀kùn ilé náà, àní ti tẹ́ḿpìlì.

51. Nígbà tí gbogbo iṣẹ́ tí Sólómónì ọba ṣe fún ilé Olúwa parí, ó mú gbogbo nǹkan tí Dáfídì baba rẹ̀ ti yà sí mímọ́ wá; fàdákà, wúrà àti ohun èlò, ó sì fi wọ́n sínú ìṣúra ilé Olúwa.

Ka pipe ipin 1 Ọba 7