Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 4:11-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Beni-Ábínádábù, ní Napoti Dórì; òun ni ó fẹ́ Táfátì ọmọbìnrin Sólómónì ní aya.

12. Báánà ọmọ Áhílúdì, ní Táánákì àti Mégídò, àti ní gbogbo Bétísánì tí ń bẹ níhà Saritanà níṣàlẹ̀ Jésérẹ́lì, láti Bétísánì dé Abeli-Méhólà títí dé ibi tí ń bẹ ní ìkọjá Jókínéámù;

13. Bẹni-Gébérì ní Rámótì-Gílíádì; tirẹ̀ ni àwọn ìletò Jáírì ọmọ Mànásè tí ń bẹ ní Gílíádì, tirẹ̀ sì ni agbégbé Ágóbù, tí ń bẹ ní Básánì, ọgọ́ta (60) ìlú tí ó tóbi pẹ̀lú odi tí ẹnu ọ̀nà rẹ̀ jẹ́ irin.

14. Áhínádábù ọmọ Ídò ní Máhánáímù

15. Áhímásì ní Náfítalì; ó fẹ́ Básémátì ọmọbìnrin Sólómónì ní aya;

16. Báánà ọmọ Húṣáì ní Ásérì àti ní Álótì;

17. Jèhósáfátì ọmọ Párúhà ni ó wà ní Ísákárì;

18. Síméì ọmọ Élà ni Bẹ́ńjámínì;

19. Gébérì ọmọ Úrì ní Gílíádì; orílẹ̀ èdè Ṣíhónì ọba àwọn ará Ámórì àti orílẹ̀ èdè Ógù ọba Básánì. Òun nìkan ni ìjòyè lórí ilẹ̀ náà.

20. Àwọn ènìyàn Júdà àti ti Ísírẹ́lì pọ̀ gẹ́gẹ́ bí iyanrìn tí ń bẹ ní etí òkun; wọ́n ń jẹ, wọ́n sì ń mu, wọ́n sì ń yọ ayọ̀.

21. Sólómónì sì ń ṣàkóso lórí gbogbo àwọn ijọba láti odò Éjíbítì títí dé ilẹ̀ àwọn ará Fílístínì, àti títí dé etí ilẹ̀ Éjíbítì. Àwọn orílẹ̀ èdè yìí ń mú owó òde wá, wọ́n sì ń sin Sólómónì ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.

22. Oúnjẹ Sólómónì fún ọjọ́ kan jásí ọgbọ̀n (30) ìyẹ̀fun kíkúná àti ọgọ́ta (60) òṣùwọ̀n ìyẹ̀fun,

23. Màlúù mẹ́wàá (10) tí ó sanra, àti ogún (20) màlúù láti inú pápá wá, àti ọgọ́rùn-ún (100) àgùntàn àti ewúrẹ́, láìka àgbọ̀nrín àti egbin, àti ogbúgbu, àti ẹyẹ tí ó sanra.

Ka pipe ipin 1 Ọba 4