Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 20:18-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Ó sì wí pé, “Bí wọ́n bá bá ti àlàáfíà jáde wá, ẹ mú wọn láàyè; bí ti ogun ni wọ́n bá bá jáde, ẹ mú wọn láàyè.”

19. Àwọn ìjòyè kékèké wọ̀nyí ti àwọn ìjòyè ìgbéríko jáde ti ìlú wá, àti ogun tí ó tẹ̀lé wọn.

20. Olúkúlùkù sì pa ọkùnrin kọ̀ọ̀kan. Àwọn ará Árámù sì sá, Ísírẹ́lì sì lépa wọn. Ṣùgbọ́n Bẹni-Hádádì ọba Árámù sì sálà lórí ẹsin pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́sin.

21. Ọba Ísírẹ́lì sì jáde lọ, ó sì kọlu àwọn ẹsin àti kẹ̀kẹ́, ó pa àwọn ará Árámù ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.

22. Lẹ́yìn náà, wòlíì náà sì wá sọ́dọ̀ ọba Ísírẹ́lì, ó sì wí pé, “Lọ, mú ara rẹ gírí, kí o sì mọ̀, kí o sì wo ohun tí ìwọ yóò ṣe, nítorí ní àmọ́dún ọba Árámù yóò tún gòkè tọ̀ ọ́ wá.”

23. Àwọn ìránṣẹ́ ọba Árámù sì wí fún un pé, “Ọlọ́run wọn, Ọlọ́run òkè ni. Ìdí nìyìí tí wọ́n ṣe ní agbára jù wá lọ. Ṣùgbọ́n bí a bá bá wọn jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ dájúdájú.

24. Nǹkan yìí ni kí o sì ṣe: Mú àwọn ọba kúrò, olúkúlùkù kúrò ní ipò rẹ̀, kí o sì fi olórí ogun sí ipò wọn.

Ka pipe ipin 1 Ọba 20