Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 11:8-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe bẹ́ẹ̀ fún gbogbo àwọn àjèjì obìnrin rẹ̀, ẹni tí ń sun tùràrí, tí wọ́n sì ń rúbọ fún òrìṣà wọn.

9. Olúwa bínú sí Sólómónì nítorí ọkàn rẹ̀ ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì, tí ó ti fi ara hàn án lẹ́ẹ̀méjì.

10. Bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti kìlọ̀ fún Sólómónì kí ó má ṣe tọ àwọn Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn, ṣùgbọ́n Sólómónì kò pa àṣẹ Olúwa mọ́.

11. Nítorí náà Olúwa wí fún Sólómónì pé, “Nítorí bí ìwọ ti ṣe nǹkan yìí, tí ìwọ kò sì pa májẹ̀mú mi àti àṣẹ mi mọ́, tí mo ti pa láṣẹ fún ọ, dájúdájú èmi yóò fa ìjọba ya kúrò lọ́wọ́ rẹ, èmi yóò sì fi fún ẹlòmìíràn.

12. Ṣùgbọ́n, nítorí Dáfídì baba rẹ, Èmi kì yóò ṣe é ní ọjọ́ rẹ. Èmi yóò fà á ya kúrò lọ́wọ́ ọmọ rẹ.

13. Síbẹ̀ èmi kì yóò fa gbogbo ìjọba náà ya, ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀yà kan fún ọmọ rẹ nítorí Dáfídì ìránṣẹ́ mi, àti nítorí Jérúsálẹ́mù tí èmi ti yàn.”

14. Nígbà náà ni Olúwa gbé ọ̀ta kan dìde sí Sólómónì, Hádádì ará Édómù ìdílé ọba ni ó ti wá ní Édómù.

15. Ó sì ṣe, nígbà tí Dáfídì wà ní Édómù, Jóábù olórí ogun sì gòkè lọ láti sìn àwọn ọmọ ogun Ísírẹ́lì ti a pa lójú ogun, ó sì pa gbogbo ọkùnrin Édómù.

16. Nítorí Jóábù àti gbogbo Ísírẹ́lì sì dúró níbẹ̀ fún oṣù mẹ́fà, títí wọ́n fi pa gbogbo ọkùnrin Édómù run.

17. Ṣùgbọ́n Hádádì sá lọ sí Éjíbítì pẹ̀lú àwọn ará Édómù tí wọ́n jẹ́ ìránṣẹ́ bàbá rẹ̀. Hádádì sì wà ní ọmọdé nígbà náà.

Ka pipe ipin 1 Ọba 11