Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 4:21-35 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Àwọn ọmọ Ṣélà ọmọ Júdà:Érì baba Lékà, Ládà baba Máréṣà àti àwọn ìdílé ilé àwọn tí ń wun aṣọ oníṣẹ́ ní Bẹti-Áṣíbéà.

22. Tókímù, ọkùnrin kósébà, àti Jóáṣì àti sáráfù, olórí ní Móábù àti Jáṣúbì Léhémù. (Àkọsílẹ̀ yìí sì wà láti ìgbà àtijọ́).

23. Àwọn sì ni amọ̀kòkò tí ń gbé ní Nítaímù àti Gédérà; wọ́n sì dúró níbẹ̀ wọ́n sì ń sisẹ́ fún ọba.

24. Àwọn Ọmọ Síméónì:Némúélì, Jámínì, Járíbì, Ṣérà àti Ṣáúlì;

25. Ṣálúmù sì jẹ́ ọmọ Ṣáúlì, Míbísámù ọmọ Rẹ̀ Miṣima ọmọ Rẹ̀.

26. Àwọn ọmọ Míṣímà:Hámúélì ọmọ Rẹ̀ Sákúrì ọmọ Rẹ̀ àti Ṣíméhì ọmọ Rẹ̀.

27. Síméì sì ní ọmọkùnrin mẹ́rìndínlógún àti ọmọbìnrin mẹ́fà, ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀gbọ́n Rẹ̀ ọkùnrin kò ní ọmọ púpọ̀; Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìdílé wọn kò sì pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn Júdà.

28. Wọ́n sì ń gbé ní Béríṣébà, Móládà, Hásárì Ṣúálì,

29. Bílà, Ésémù, Tóládì,

30. Bétúélì, Hórímà, Síkílágì,

31. Bẹti máríkóbótì Hórímà; Hásárì Ṣúsímù, Bẹti Bírì àti Ṣáráímì. Àwọn wọ̀nyí ni ìlú wọn títí di ìgbà ọba Dáfídì,

32. agbégbé ìlú wọn ni Étamù Háínì, Rímónì, Tókénì, Áṣánì àwọn ìlú márùnún

33. Àti gbogbo ìletò tí ó wà ní agbégbé àti gẹ́gẹ́ bí ó ti dé Bálì Àwọn wọ̀nyí ni ibùgbé wọn, wọ́n sì pa ìwé ìtàn ìdílé mọ́.

34. Méṣóbábù Jámilékì, Jóṣáì ọmọ Ámásáyà,

35. Jóẹ́lì, Jéhù ọmọ Jósíbíà, ọmọ Ṣéráíáyà, ọmọ Ásíẹ́lì,

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 4