Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 28:3-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún mi pé: Ìwọ kò gbodò kọ́ ilé fún orúkọ mi, nítorí ìwọ jẹ́ jagunjagun, ìwọ sì ti tàjẹ̀sílẹ̀.

4. “Síbẹ̀ Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì yàn mí láti gbogbo ìdílé láti jẹ́ ọba lórí Ísírẹ́lì, títí láé. Ó yan Júdà gẹ́gẹ́ bí olórí, àti láti ilé Júdà, ó yan ìdílé mi, àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ baba à mí, ó tẹ́ Ẹ lọ́rùn láti fi mí ṣe ọba lórí gbogbo Ísírẹ́lì.

5. Ninú gbogbo àwọn ọmọ mi pẹ̀lú Olúwa ti fún mi ní púpọ̀, ó ti yan ọmọ mi Sólómónì láti jòkó lórí ìtẹ́ ìjọba ti Olúwa lóri Isírẹ́lì.

6. Ó wí fún mi pé, Sólómónì ọmọ rẹ ni ẹni tí yóò kọ́ ilé mi àti àwọn ààfin mi, Nítorí tí èmi ti yàn án láti ṣe ọmọ mi èmi yóò sì jẹ́ baba a Rẹ̀.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 28