Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 28:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Dáfídì pe gbogbo àwọn oniṣẹ́ ti Ísírẹ́lì láti pẹ́jọ ní Jérúsálẹ́mù: Àwọn ìjòyè lórí àwọn ẹ̀yà, àwọn alákòóṣo ìpín nínú iṣẹ́ bí ọba, àwọn alákòóṣo ẹgbẹgbẹ̀rún àti àwọn alákòóṣo ọrọrún àti àwọn onísẹ́ tí ó wà ní ìdí bíbojútó gbogbo àwọn ẹrù àti ohun ọ̀sìn tí ó jẹ́ ti ọba àti àwọn ọmọ Rẹ̀ pẹ̀lú ààfin àwọn onísẹ́ ààfin, àwọn ọkùnrin alágbára àti gbogbo àwọn ògbójú jagunjagun lápapọ̀.

2. Ọba Dáfídì dìde dúró ní ẹṣẹ̀ Rẹ̀, o sì wí pé Fetísílẹ̀ sí mi, ẹyin ará mi àti ẹ̀yin ènìyàn mi. Èmi ní o ni ọkàn mi láti kọ́ ilé gẹ́gẹ́ bí ibi ìsinmi fún àpótí ẹ̀rí májẹ̀mú tí Olúwa fún àpótí ìtìsẹ̀ Ọlọ́run wa, èmi sì gbèrò láti kọ́ ọ.

3. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún mi pé: Ìwọ kò gbodò kọ́ ilé fún orúkọ mi, nítorí ìwọ jẹ́ jagunjagun, ìwọ sì ti tàjẹ̀sílẹ̀.

4. “Síbẹ̀ Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì yàn mí láti gbogbo ìdílé láti jẹ́ ọba lórí Ísírẹ́lì, títí láé. Ó yan Júdà gẹ́gẹ́ bí olórí, àti láti ilé Júdà, ó yan ìdílé mi, àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ baba à mí, ó tẹ́ Ẹ lọ́rùn láti fi mí ṣe ọba lórí gbogbo Ísírẹ́lì.

5. Ninú gbogbo àwọn ọmọ mi pẹ̀lú Olúwa ti fún mi ní púpọ̀, ó ti yan ọmọ mi Sólómónì láti jòkó lórí ìtẹ́ ìjọba ti Olúwa lóri Isírẹ́lì.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 28